19. Àwọn igi tí yóò kù nínú igbóo rẹ̀yóò kéré níye,tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.
20. Ní ijọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Ísírẹ́lìÀwọn tí ó yè ní ilée Jákọ́bùkò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náàtí ó lùwọ́n bolẹ̀ṣùgbọ́n yóò gbẹ́kẹ̀lé OlúwaẸni Mímọ́ Ísírẹ́lì.
21. Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jákọ́bùyóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.
22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn an rẹ, ìwọ Ísírẹ́lìdàbí yanrìn ní òkun,ẹni díẹ̀ ni yóò padà.A ti pàṣẹ ìparunà kún wọ́ sílẹ̀ àti òdodo.
23. Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú-un ṣẹ,ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórígbogbo ilẹ̀ náà.
24. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,“Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Ṣíhónì,Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Ásíríà,tí ó ń fi ọ̀pá lù yín,tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tìyín bíÉjíbítì ti ṣe.
25. Láìpẹ́, ìbínú mi síi yín yóò wá sí òpinn ó sì dojú ìrunú mi kọ wọ́n,fún ìparun wọn.”