Àìsáyà 10:17-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ìmọ́lẹ̀ Ísírẹ́lì yóò di iná,ẹni Mímọ́ an wọn ahọ́n iná,ní ijọ́ kan ṣoṣo yóò jó yóò sì runàti ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n.

18. Gbogbo ẹwà igbóo rẹ̀, àti àwọn pápá ọlọ́ràágbogbo rẹ̀ ni yóò run pátapáta,gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó sàìṣàn ti í ṣòfò dànù.

19. Àwọn igi tí yóò kù nínú igbóo rẹ̀yóò kéré níye,tí ọ̀dọ́mọdé yóò fi le kọ̀ wọ́n sílẹ̀.

20. Ní ijọ́ náà, àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Ísírẹ́lìÀwọn tí ó yè ní ilée Jákọ́bùkò ní gbẹ́kẹ̀lé ẹni náàtí ó lùwọ́n bolẹ̀ṣùgbọ́n yóò gbẹ́kẹ̀lé OlúwaẸni Mímọ́ Ísírẹ́lì.

21. Àwọn ìyókù yóò padà, àwọn ìyókù ti Jákọ́bùyóò padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Alágbára.

22. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn an rẹ, ìwọ Ísírẹ́lìdàbí yanrìn ní òkun,ẹni díẹ̀ ni yóò padà.A ti pàṣẹ ìparunà kún wọ́ sílẹ̀ àti òdodo.

23. Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú-un ṣẹ,ìparun tí a ti pàṣẹ rẹ̀ lórígbogbo ilẹ̀ náà.

24. Nítorí náà, báyìí ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí,“Ẹ̀yin ènìyàn mi tí ó ń gbé Ṣíhónì,Ẹ má ṣe bẹ̀rù àwọn Ásíríà,tí ó ń fi ọ̀pá lù yín,tí wọ́n sì ń gbé ọ̀gọ tìyín bíÉjíbítì ti ṣe.

Àìsáyà 10