Àìsáyà 1:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogunbá sẹ́ díẹ̀ kù fún wà,a ò bá ti rí bí Sódómù,a ò bá sì ti dàbí Gòmórà.

10. Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa,ẹ̀yin aláṣẹ Sódómù,tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa,ẹ̀yin ènìyàn Gòmórà!

11. “Ọpọ̀lọpọ̀ ẹbọ yínkín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí.“Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísunti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa,Èmi kò ní inú dídùnnínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntànàti ti orúkọ.

12. Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi,ta ni ó bèèrè èyí lọ́wọ́ ọ yín,Gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?

13. Ẹ má mú ọrẹ aṣán wá mọ́!Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi,oṣù tuntun, ọjọ́ ọ̀sẹ̀ àti àwọn àpèjọÈmi kò lè faradà àpèjọ ibi yín wọ̀nyí.

Àìsáyà 1