Àìsáyà 1:22-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Sílífà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́,ààyò wáìnì rẹ la ti bomi là.

23. Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín,akẹgbẹ́ àwọn olè,gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri.Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba,ẹjọ́ opó kì í sìí dé iwájú wọn.

24. Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogunAlágbára kanṣoṣo tí Ísírẹ́lì sọ wí pé:“Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá min ó sì gbẹ̀ṣan lára àwọn ọ̀tá mi.

Àìsáyà 1