2 Sámúẹ́lì 9:11-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ṣíbà sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Olúwa mi ọba ti pa láṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Méfibóṣétì, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, Gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”

12. Méfibóṣétì sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Míkà. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Síbà ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Méfibóṣétì.

13. Méfibóṣétì sì ń gbé ní Jérúsálẹ́mù: òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ́ ọba; òun sì yarọ ní ẹṣẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.

2 Sámúẹ́lì 9