2 Sámúẹ́lì 8:10-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. Tóì sì rán Jórámù ọmọ rẹ̀ sí Dáfídì ọba, láti kí i, àti láti súre fún un, nítorí pé ó tí bá Hadadésérì jagun, ó sì ti pa á: nítorí tí Hadadésérì sáà ti bá Tóù jagun. Jórámù sì ni ohun èlò fàdákà, àti ohun èlò wúrà, àti ohun èlò idẹ ní ọwọ́ rẹ̀.

11. Dáfídì ọba sì fi wọ́n fún Olúwa pẹ̀lú fàdákà, àti wúrà tí ó yà sí mímọ́, èyí tí ó ti gbà lọ́wọ́ àwọn orilẹ̀-èdè tí ó ti ṣẹ́gun.

12. Lọ́wọ́ Síría àti lọ́wọ́ Móábù àti lọ́wọ́ àwọn ọmọ Ámónì, àti lọ́wọ́ àwọn Fílístínì, àti lọ́wọ́ Ámálékì, àti nínú ìkógun Hadadésérì ọmọ Réhóbù ọba Sóbà.

13. Dáfídì sì ní òkìkí gidigidi nígbà tí ó padà wá ilé láti ibi pípa àwọn ará Síríà ní àfonífojì iyọ̀, àwọn tí o pa jẹ́ ẹgbaàsán ènìyàn.

2 Sámúẹ́lì 8