9. Dáfídì sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dáfídì. Dáfídì mọ ìgànná yí i ká láti Mílò wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
10. Dáfídì sì ń pọ̀ si i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
11. Hírámù ọba Tírè sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dáfídì, àti igi kédárì, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dáfídì.
12. Dáfídì sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jọba lórí Ísírẹ́lì, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Ísírẹ́lì àwọn ènìyàn rẹ̀.
13. Dáfídì sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jérúsálẹ́mù wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hébírónì bọ̀: wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dáfídì.
14. Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jérúsálẹ́mù; Ṣamímúà àti Sóbábù, àti Nátanì, àti Sólómónì.
15. Àti Íbéhárì, àti Élíṣúà, àti Néfégì, àti Jáfíà.
16. Àti Élíṣámà, àti Élíádà, àti Élífélétì.