2 Sámúẹ́lì 3:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ábínérì sì bínú gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ti Iṣibósẹ́tì sọ fún un, ó sì wí pé, “Èmi jẹ́ bí orí ajá ti Júdà bí? Di òní yìí ni mọ ṣàáánú fún ìdílé Ṣọ́ọ̀lù bàbá rẹ, àti fún àwọn arákùnrin rẹ̀, àti fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, tí èmi kò sì fi ọ́ lé Dáfídì lọ́wọ́, ìwọ sì kà ẹ̀ṣẹ̀ sí mí lọ́rùn nítorí obìnrin yìí lóní?

9. Bẹ́ẹ̀ ni kí Ọlọ́run ó ṣe Ábínérì, àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí Olúwa ti búra fún Dáfídì, bí èmi kò ní ṣe bẹ́ẹ̀ fún un.

10. Láti mú ìjọba náà kúrò ní ìdílé Ṣọ́ọ̀lù, àti láti gbé ìtẹ́ Dáfídì kalẹ̀ lorí Ísírẹ́lì, àti lórí Júdà, láti Dánì títí ó fi dé Bíáṣébà!”

11. Òun kò sì lè dá Ábínérì lóhùn kan nítorí tí ó bẹ̀rù rẹ̀.

2 Sámúẹ́lì 3