2 Sámúẹ́lì 23:12-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

12. Òun sì dúró láàrin méjì ilẹ̀ náà, ó sì gbàá sílẹ̀, ó sì pa àwọn Fílístínì Olúwa sì ṣe ìgbàlà ńlá.

13. Àwọn mẹ́ta nínú ọgbọ̀n olórí sì sọkalẹ̀, wọ́n sì tọ Dáfídì wá ní àkókò ìkórè nínú ihò Ádúlámù: ọ̀wọ́ àwọn Fílístínì sì dó sí àfonífojì Réfáímù.

14. Dáfídì sì wà nínú odi, ibùdó àwọn Fílístínì sì wà ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù nígbà náà.

15. Dáfídì sì ń pòùngbẹ, ó wí bayìí pé, “Ta ni yóò fún mi mu nínú omí kàǹga tí ń bẹ ní Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, èyí tí ó wà ní ìhà ẹnu bodè.”

2 Sámúẹ́lì 23