2 Sámúẹ́lì 22:44-49 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

44. “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi,ìwọ pá mí mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè.Àwọn ènìyàn tí èmi kòì tí mọ̀ yóò máa sìn mí.

45. Àwọn àlejò wá láti tẹríba fún mi;bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọn á sì gbọ́ tèmi.

46. Àyà yóò pá àwọn àlejò,wọn ó sì fi ìbẹ̀rù sá kúrò níbi kọ́lọ́fín wọn.

47. “Olúwa ń bẹ́; olùbùkún sì ni àpáta mi!Gbígbéga sì ni Ọlọ́run àpáta ìgbàlà mi.

48. Ọlọ́run ni ẹni tí ń gbẹ̀san mi,àti ẹni tí ń rẹ àwọn ènìyàn sílẹ̀ lábẹ́ mi.

49. Àti ẹni tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀ta mi.Ìwọ sì gbé mi sókè ju àwọn tí ó dìde sí mi lọ;ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọkùnrin oníwà ipá.

2 Sámúẹ́lì 22