22. Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́,èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.
23. Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi;àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.
24. Èmi sì wà nínú ìwà-títọ́ sí í,èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.
25. Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,gẹ́gẹ́ bí ìwà-mímọ́ mi níwájú rẹ̀.
26. “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú,àti fún ẹni-ìdúró-ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró-ṣinṣin ní òdodo.