2 Sámúẹ́lì 14:29-32 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

29. Ábúsálómù sì ránṣẹ́ sí Jóábù, láti rán an sí ọba: ṣùgbọ́n òun kò fẹ́ wá sọ́dọ̀ rẹ̀; ó sì ránṣẹ́ lẹ́ẹ̀kejì òun kò sì fẹ́ wá.

30. Ó sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wò ó, oko Jóábù gbé ti èmi, ó sì ní ọkà níbẹ̀; ẹ lọ kí ẹ sì tinábọ̀ ọ́.” Àwọn ìrànṣẹ́ Ábúsálómù sì tinábọ oko náà.

31. Jóábù sì dìde, ó sì tọ Ábúsálómù wá ní ilé, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ fi tinábọ oko mi?”

32. Ábúsálómù sì dá Jóábù lóhùn pé, “Wò ó, èmi ránṣẹ́ sí ọ, wí pé, ‘Wá níhìn-ín yìí, èmi ó sì rán ọ lọ sọ́dọ̀ ọba, láti béèrè pé, “Kí ni èmi ti Géṣúrì wá si? Ìbá sàn fún mí bí ó ṣe pé èmi wà lọ́hùn-ún ṣíbẹ̀!” ’ Ǹjẹ́ nísinsin yìí jẹ́ kí èmi lọ síwájú ọba bí ó bá sì ṣe ẹ̀bi ń bẹ nínú mi, kí ó pa mí.”

2 Sámúẹ́lì 14