2 Sámúẹ́lì 11:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Lẹ́yìn ìgbà tí ọdún yípo, ní àkókò ìgbà tí àwọn ọba náà ń jáde ogun, Dáfídì sì rán Jóábù, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, àti gbogbo Ísírẹ́lì; wọ́n sì pa àwọn ọmọ Ámónì, wọ́n sì dó ti Rábà. Dáfídì sì jókòó ní Jérúsálẹ́mù.

2. Ó sì ṣe, ní ìgbà àṣálẹ́ kan, Dáfídì sì díde ní ibùsùn rẹ̀, ó sì ń rìn lórí òrùlé ilé ọba, láti orí òrùlé náà ni ó sì rí obìnrin kan tí ó ń wẹ̀ ara rẹ̀; obìnrin náà sì ṣe arẹwà lójú láti wò.

3. Dáfídì sì ránṣẹ́ ó sì béèrè obìnrin náà. Ẹnìkan sì wí pé, Èyí ha kọ́ ni Báṣébà, ọmọbìnrin Élíámì, aya Úráyà ará Hítì.

2 Sámúẹ́lì 11