15. Nígbà tí àwọn ará Síríà sì ríi pé Àwọn ṣubú níwájú Ísírẹ́lì: wọ́n sì kó ara wọn jọ
16. Hadadésérì sì ránṣẹ́, ó sì mú àwọn Síríà tí ó wà ní òkè odò jáde wá: wọ́n sì wá sí Hélámì; Sóbákì olórí ogun Hedareṣérì sì ṣe olórí wọn.
17. Nígbà tí a sọ fún Dáfídì, ó sì kó gbogbo Ísírẹ́lì jọ, wọ́n sì kọjá Jọ́dánì, wọ́n sì wá sí Hélámì, Àwọn ará Síríà sì tẹ́ ogun kọjú sí Dáfídì, wọ́n sì bá a jà.
18. Àwọn ará Síríà sì sá níwájú Ísírẹ́lì, Dáfídì sì pa nínú àwọn ará Síríà ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin àwọn oníkẹ̀kẹ́, àti ọ̀kẹ́ méjì ẹlẹ́ṣin, wọ́n sì kọlu Sóbákì olórí ogun wọn, ó sì kú níbẹ́.
19. Nígbà tí gbogbo àwọn ọba tí ó wà lábẹ́ Hadadésérì sì ríi pé wọ́n di bíbì ṣubú níwájú Ísírẹ́lì, wọ́n sì bá Ísírẹ́lì làjà, wọ́n sì ń sìn wọ́n.Àwọn ará Síríà sì bẹ̀rù lati máa ran àwọn ọmọ Ámónì lọ́wọ́ mọ́.