1. Jéhórámù ọmọ Áhábù ó sì di ọba Ísírẹ́lì ní Ṣamáríà ní ọdún kejìdínlógún ti Jéhósáfátì ọba Júdà, ó sì jọba fún ọdún méjìlá.
2. Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti bàbá rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Báálì tí baba rẹ̀ ti ṣe.
3. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbóámù ọmọ Nébátì, tí ó ti fi Ísírẹ́lì bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.