9. Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí baba rẹ̀ ti ṣe.
10. Ní àkókò náà àwọn ìjòyè Nebukadinéṣárì ọba Bábílónì wá sílẹ̀ Jérúsálẹ́mù wọ́n sì gbé dófì kalẹ̀ fún un,
11. Nebukadinéṣárì fúnrarẹ̀ wá sókè sí ìlú nígbà tí àwọn ìjòyè fi ogun dótì í.
12. Jéhóíákímù ọba Júdà àti ìyá rẹ̀ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ìwẹ̀fà àti àwọn ìjòyè gbogbo wọn sì jọ̀wọ́ ara wọn fún un.Ní ọdún kẹjọ ìjọba rẹ̀ ti ọba Bábílónì ó mú Jéhóíákínì ẹlẹ́wọ̀n.
13. Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ Nebukadinéṣárì kó gbogbo ìṣúra láti inú ilé Olúwa àti láti ilé ọba, ó sì mú u lọ gbogbo ohun èlò wúrà ti Ṣólómónì ọba Ísírẹ́lì