2 Ọba 18:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọdún kẹta Hóséà ọmọ Élà ọba Ísírẹ́lì, Heṣekíàyà ọmọ Áhásì ọba Júdà bẹ̀rẹ̀ ìjọba.

2. Ó jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n nígbà tí ó ti di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jérúsálẹ́mù fún ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. Orúkọ ìyá rẹ̀ a sì máa jẹ́ A bì ọmọbìnrin Ṣakaríàyà.

3. Ó sì ṣe ohun tí ó dára níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí i baba rẹ̀ Dáfídì ti ṣe.

4. Ó mú ibi gíga náà kúrò, ó sì fọ́ òkúta àwọn ère ó sì gé àwọn ère lulẹ̀ ó sì fọ́ ejò idẹ náà túútúú tí Móṣè ti ṣe, títí di ọjọ́ tí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ń sun tùràrí sí. (Wọ́n sì pè é ní Néhúṣítanì.)

2 Ọba 18