22. Òun ni ẹni tí ó tún Élátì kọ́, ó sì dá a padà sí Júdà lẹ́yìn tí Ámásáyà ti sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀.
23. Ní ọdún kẹẹ̀dógún tí Ámásáyà ọmọ Jóásì ọba Júdà, Jéróbóámù ọmọ Jéhóásì ọba Ísírẹ́lì di ọba ní Ṣamáríà, ó sì jọba fún ọ̀kànlélógójì ọdún.
24. Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa kò sì yípadà kúrò nínú ọ̀kankan nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbóámù ọmọ Nébátì. Èyí tí ó ti fa Ísírẹ́lì láti dá.