1. Ní ọdún keje tí Jéhù, Jóásì di ọba, ó sì jọba ní Jérúsálẹ́mù fún ogójì ọdún. Orúkọ ìyá a rẹ̀ a máa jẹ́ Síbíyà: Ó wá láti Beeriṣébà.
2. Jóásì ṣe ohun tí ó tọ́ ní ojú Olúwa ní gbogbo ọdún tí Jéhóíádà àlùfáà fi àsẹ fún un.
3. Àwọn ibi gíga, bí ó ti wù kí ó rí, a kò sí wọn ní ìdí; Àwọn ènìyàn sì tẹ̀ṣíwájú láti máa rú ẹbọ àti sísun tùràrí níbẹ̀.