2 Ọba 10:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nísinsìn yìí, Áhábù sì ní àádọ́rin ọmọkùnrin ní ìdílé rẹ̀ ní Ṣamáríà. Bẹ́ẹ̀ ni, Jéhù kọ lẹ́tà, ó sì fi wọ́n ránṣẹ́ sí Samáríà: sí àwọn oníṣẹ́ Jésérẹ́lì, sí àwọn àgbààgbà àti sí àwọn olùtọ́jú àwọn ọmọ Áhábù. Ó wí pé,

2. “Ní kété tí lẹ́tà bá ti dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí àwọn ọmọ ọ̀gá a rẹ wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ sì ní àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ẹṣin, ìlú olódi kan pẹ̀lú ohun ìjà,

3. yan èyí tí ó dára àti èyí tí ó níye jùlọ nínú àwọn ọmọkùnrin ọ̀gá à rẹ, kí o sì gbé e lé orí ilé baba a rẹ̀. Nígbà náà, kí o sì jà fún, ilé ọ̀gá à rẹ.”

2 Ọba 10