2 Kọ́ríńtì 4:5-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nítórí àwa kò wàásù àwa tìkárawa, bí kò se Kírísítì Jésù Olúwa; àwa tikarawa sì jẹ́ ẹrú yín nítorí Jésù.

6. Nítorí Ọlọ́run ni ẹni tí ó wí pé, “Kí ìmọ́lẹ̀ ó mọ́lẹ̀ láti inú òkùnkùn jáde,” òun ní ó ti ń mọ́lẹ̀ lọ́kan wa, láti fún wa ní ìmọ́lẹ̀ ìmọ̀ ògo Ọlọ́run ní ojú Jésù Kírísítì.

7. Ṣùgbọ́n àwa ní ìṣúra yìí nínú ohun èlò àìmọ́, kí ọlá ńlá agbára náà lè jẹ́ ti Ọlọ́run, kí ó má ṣe ti ọ̀dọ̀ wa wá.

8. A ń pọ́n wa lójú níhà gbogbo, ṣùgbọ́n ara kò ni wá: a ń dàámú wa, ṣùgbọ́n a kò sọ ìrètí nù.

2 Kọ́ríńtì 4