2 Kọ́ríńtì 11:13-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nítorí irú àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni àwọn èkè Àpósítélì àwọn ẹni ti ń ṣiṣẹ́ ẹ̀tàn, tí ń pa wọ́n dà di Àpósítélì Kírísítì.

14. Kì í sì í ṣe ohun ìyanu; nítorí Sátanì, tìkáraarẹ̀ ń pa ara rẹ̀ dà bí ańgẹ́lì ìmọ́lẹ̀.

15. Nítorí náà kì í ṣe ohun ńlá bí àwọn ìrànṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú bá pa ara wọn dà bí àwọn ìrànṣẹ́ òdodo; ìgbẹ́yìn àwọn ẹni tí yóò rí gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn.

16. Mo sì tún wí pé, kí ẹnikẹ́ni má ṣe rò pé òmùgọ̀ ni mí; ṣùgbọ́n bí bẹ́ẹ̀ bá ni, ẹ gbà mí bí òmùgọ̀ kí èmi lè gbé ara mi ga díẹ̀.

17. Ohun tí èmi ń sọ, èmi kò sọ ọ́ nípa ti Olúwa, ṣùgbọ́n bí òmùgọ̀ nínú ìgbẹ́kẹ̀lé ìṣògo yìí.

2 Kọ́ríńtì 11