8. Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Dáfídì baba mi pé, ‘Nítorí tí ó wà ní ọkàn rẹ láti kọ́ tẹ́ḿpìlì yìí fún orúkọ mi, ìwọ ṣe ohun dáradára láti ní èyí ní ọkàn rẹ̀.
9. Ṣùgbọ́n síbẹ̀, ìwọ kọ́ ni yóò kọ́ tẹ́ḿpìlì náà, bí kò ṣe ọmọ rẹ, ẹni tí o jẹ́ ẹran ara àti ẹ̀jẹ̀ rẹ: òun ni yóò kọ́ tẹ́ḿpìlì fún orúkọ mi.’
10. “Olúwa sì ti mú ìléri rẹ̀ ṣẹ. Èmi ti dìde ní ipò Dáfídì baba mi, a sì gbé mi ka ìtẹ́ Ísírẹ́lì, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ṣe ìlérí, èmi sì ti kọ́ tẹ́ḿpìlì fún orúkọ Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.