41. “Ǹjẹ́ nísinsin yìí dìdé, Olúwa Ọlọ́run mi, sí ibi ìsinmi rẹ,ìwọ àti àpótí ẹ̀rí agbára rẹ.Jẹ́ kí àwọn àlùfáà, Olúwa Ọlọ́run mi, kí o wọ̀ wọ́n lásọ pẹ̀lú ìgbàlà,jẹ́ kí àwọn àyànfẹ́ kí inú wọn kí ó dùn nínú ilé rẹ.
42. Olúwa Ọlọ́run mi, má ṣe kọ̀ ẹni àmìn òróró rẹ.Rántí ìfẹ́ ńlá tí ó ṣe ìlérí fún Dáfídì ìránṣẹ́ rẹ.”