25. Ámásíà ọmọ Jóáṣì ọba Júdà gbé fún ọdun mẹ́ẹ̀dógún lẹ́yìn ikú Jehóaṣì ọmọ Jehóáháṣì ọba Ísírẹ́lì.
26. Fún ti iṣẹ́ mìíràn ti ìjọba Ámásíà láti ìbẹ̀rẹ̀ dé ìparí, ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé àwọn ọba Júdà àti Ísírẹ́lì?
27. Láti ìgbà tí Ámásíà ti yípadà kúrò láti máa tẹ̀lé Olúwa, wọ́n dìtẹ̀ síi ní Jérúsálẹ́mù, ó sì sálọ sí Lákíṣì ṣùgbọ́n, wọ́n rán àwọn ọkùnrin tẹ̀lé e lọ sí Lákiṣì, wọ́n sì paá síbẹ̀.
28. A gbé e padà pẹ̀lú ẹsin. A sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú ńlá ti Júdà.