10. Títí di ọjọ́ òní ni Édómù ti wà ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Júdà.Líbínà ṣọ̀tẹ̀ ní àkọ́kọ́ náà, nítorí tí Jéhórámì ti kọ Olúwa sílẹ̀, Ọlọ́run àwọn baba a rẹ̀.
11. Òun pẹ̀lú ti kọ́ àwọn ibi gíga lórí àwọn òkè Júdà. Ó sì ti fà á kí àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù ó se àgbérè pẹ̀lú ara wọn. Ó sì ti jẹ́ kí wọn ó ṣáko lọ.
12. Jóhórámì gba ìwé láti ọwọ́ Èlíjà wòlíì, tí ó wí pé:“Èyí ní ohun tí Olúwa, Ọlọ́run baba à rẹ Dáfídì wí: ‘Ìwọ kò tí ì rìn ní ọ̀nà àwọn baba à rẹ Jèhóṣáfátì tàbí Ásà ọba Júdà.