1. Nígbà tí Jéhóṣáfátì ọba Júdà padà ní àlàáfíà sí ilé rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù,
2. Jéhù aríran, ọmọ Hánánì jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Sé ìwọ yóò máa ran ènìyàn búburú lọ́wọ́, kí o sì fẹ́ràn àwọn tí ó kórìíra Olúwa? Nítorí èyí, ìbínú Olúwa wà lórí wa.
3. Bí ó ti wù kí ó rí, ohun rere wà nínú rẹ, nítorí tí ìwọ ti mú àwọn ilé àwọn ère òrìṣà kúrò, tí o sì múra ọkàn rẹ láti wá Ọlọ́run.”