12. Ṣùgbọ́n èmi kò fi àṣẹ fún obìnrin láti máa kọ́ni, tàbí láti pàṣẹ lórí ọkùnrin, bí kò ṣe kí ó dákẹ́jẹ́.
13. Nítorí Ádámù ni a kọ́ dá, lẹ́yìn náà, Éfà.
14. Ádámù kọ́ ni a tàn jẹ, ṣùgbọ́n obìnrin náà ni a tàn tí ó sì di ẹlẹ́ṣẹ̀.
15. Ṣùgbọ́n a ó gbà àwọn obìnrin là nípa ìbímọ wọn, bí wọ́n bá dúró nínú ìgbàgbọ́, ìfẹ́, àti ìwà-mímọ́ pẹ̀lú ìwà àìrékọjá.