1 Tẹsalóníkà 4:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ìparí, ará, a sọ fún un yín bí ẹ ti ń gbé láti wu Ọlọ́run, àní gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí ń ṣe. Nísinsìnyìí, a bèèrè, a sì ń rọ̀ yín nínú Jésù Olúwa láti ṣe bẹ́ẹ̀ àti bẹ́ẹ̀ sí.

2. Nítorí pé, ẹyin mọ àṣẹ tí a pa fún yín láti ọ̀dọ̀ Olúwa Jésù.

3. Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí ẹ jẹ́ mímọ, kí ẹ sì yàgò kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àgbérè,

1 Tẹsalóníkà 4