1 Tẹsalóníkà 3:7-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Nítorí náà, ẹ̀yin ará, inú wá dùn jọjọ nínú gbogbo ìyọnu àti ìjìyà wa níbí nítorí pé àwa mọ̀ nísinsinyìí pé, ẹ̀yin sì dúró gbọn-ingbọn-in fún Olúwa.

8. Kò sí nǹkan tí a kò lè fi ara dà níwọ̀n ìgbà tí a ti mọ̀ pé, ẹ̀yin sì dúró gbọn-ingbọn-in fún Olúwa.

9. Kò ṣé é ṣe fún wa láti dá ọpẹ́ tán lọ́wọ́ Ọlọ́run nítorí ayọ̀ àti ìfẹ́ tí ó máa ń kún ọkàn wa nípa àdúrà wa fún un yín.

10. Nítorí pé àwa ń gbàdúrà fún un yín lọ̀sán-án àti lóru. Èyí yóò ràn wá lọ́wọ́ láti se àtúnṣe ibi tí ìgbàgbọ́ yín bá kù sí.

1 Tẹsalóníkà 3