1 Sámúẹ́lì 26:17-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ṣọ́ọ̀lù sì mọ ohùn Dáfídì, ó sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí Dáfídì ọmọ mi?”Dáfídì sì wí pé, “Ohùn mi ni, Olúwa mi, ọba.”

18. Òun sì wí pé, “Nítorí kín ni Olúwa mi ṣe ń lépa ìránṣẹ́ rẹ̀? Kín ni èmi ṣe? Tàbí ìwà búburú wo ni ó wà lọ́wọ́ mi.

19. Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, ọba, Olúwa mi, gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ. Bí ó bá ṣe Olúwa bá ti rú ọ sókè sí mi, jẹ́ kí òun o gba ẹbọ; ṣùgbọ́n bí o bá sì ṣe pé ọmọ ènìyàn ni, ìfibú ni kí wọn ó jásí níwájú Olúwa; nítorí tí wọn lé mi jáde lónìí kí èmi má baà ní ìpín nínú ilẹ̀ ìní Olúwa, wí pé, ‘Lọ sin àwọn ọlọ́run mìíràn.’

20. Ǹjẹ́ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ mi ó ṣàn sílẹ̀ níwájú Olúwa; nítorí ọba Ísírẹ́lì jáde láti wá ẹ̀mí mi bi ẹni ń dọdẹ àparò lórí òkè ńlá.”

21. Ṣọ́ọ̀lù sì wí pé, “Èmi ti dẹ́sẹ̀: yípadà, Dáfídì ọmọ mi: nítorí pé èmi kì yóò wa ibi rẹ mọ́, nítorí tí ẹ̀mí mi sì ti ṣe ìyebíye lójú rẹ lónìí: wò ó, èmi ti ń hùwà òmùgọ̀, mo sì ti ṣìnà jọjọ.”

1 Sámúẹ́lì 26