33. Ṣùgbọ́n Sámúẹ́lì wí pé,“Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọbẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàárin obìnrin.”Sámúẹ́lì sì pa Ágágì níwájú Olúwa ni Gílígálì.
34. Nígbà náà ni Sámúẹ́lì lọ sí Rámà, Ṣọ́ọ̀lù sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gíbéà tí Ṣọ́ọ̀lù.
35. Sámúẹ́lì kò sì padà wá mọ́ láti wo Ṣọ́ọ̀lù títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Sámúẹ́lì káànú fún Ṣọ́ọ̀lù. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Ṣọ́ọ̀lù jọba lórí Ísírẹ́lì.