1. Nígbà náà ni Sólómónì pe àwọn àgbà Ísírẹ́lì àti gbogbo àwọn olórí àwọn ẹ̀yà àti àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Ísírẹ́lì jọ papọ̀ níwájú rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù, láti gbé àpótí-ẹ̀rí májẹ̀mú Olúwa wá láti ìlú Dáfídì, tí ń ṣe Ṣíónì.
2. Gbogbo àwọn ọkùnrin Ísírẹ́lì sì pe ara wọn jọ sọ́dọ̀ Sólómónì ọba ní àkókò àjọ ọdún ní oṣù Étanímù tí íṣe osù kéje.
3. Nígbà tí gbogbo àwọn àgbà Ísírẹ́lì dé, àwọn àlùfáà sì gbé àpótí-ẹ̀rí,