1 Ọba 6:32-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

32. Àti lára ilẹ̀kùn igi ólífì náà ni ó ya àwòrán àwọn kérúbù, igi ọ̀pẹ àti ti ìtànná ewéko sí, ó sì fi wúrà bò wọ́n, ó sì tan wúrà sí ara àwọn kérúbù àti sí ara igi ọ̀pẹ.

33. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe òpó igi ólífì onígun mẹ́rin fún ilẹ̀kùn ilé náà.

34. Ó sì tún fi igi fírì ṣe ilẹ̀kùn méjì, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì ní ewé méjì tí ó yí sí ihò ìtẹ̀bọ̀.

35. Ó sì ya àwòrán kérúbù, àti ti igi ọ̀pẹ àti ti ìtànná ewéko sí ara wọn, ó sì fi wúrà bò ó, èyí tí ó tẹ́ sórí ibi tí ó gbẹ́.

36. Ó sì fi ẹṣẹṣẹ òkúta mẹ́ta gbígbẹ, àti ẹṣẹ kan ìtí kédárì kọ́ àgbàlá ti inú lọ́hùn ún.

37. Ní ọdún kẹrin ni a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lé ilẹ̀, ní oṣù Sífì.

1 Ọba 6