1 Ọba 3:15-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Sólómónì jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni.Ó sì padà sí Jérúsálẹ́mù, ó sì dúró níwájú àpótí májẹ̀mú Olúwa, ó sì rúbọ ọrẹ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àṣè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ.

16. Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbérè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ.

17. Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.

18. Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí ẹlòmíràn ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.

19. “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.

20. Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.

1 Ọba 3