1 Ọba 21:8-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ̀wé ní orúkọ Áhábù, ó sì fi èdìdì rẹ̀ dì í, ó sì fi ìwé náà ránṣẹ́ sí àwọn àgbààgbà àti àwọn ọlọ́lá tí ó ń gbé ní ìlú Nábótì pẹ̀lú rẹ̀.

9. Nínú àwọn ìwé náà, ó kọ pé:“Ẹ kéde ààwẹ̀, kí ẹ sì fi Nábótì sí ipò ọlá láàrin àwọn ènìyàn.

10. Ṣùgbọ́n kí ẹ fi ènìyàn méjì, ẹni búburú ṣíwájú rẹ̀ láti jẹ́rìí pa á wí pé, ó bú Ọlọ́run àti ọba. Nígbà náà ni kí ẹ mú u jáde, kí ẹ sì sọ ọ́ ní òkúta pa.”

11. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbààgbà àti àwọn ọlọ́lá tí wọ́n ń ṣe ará ìlú Nábótì sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Jésébélì ti ránṣẹ́ sí wọn.

1 Ọba 21