1 Ọba 21:19-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Sọ fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ǹjẹ́ ìwọ kò ti pa ènìyàn, o sì ti fi agbára gba ogún rẹ̀?’ Nígbà náà ni kí o wí fún un pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Níbi tí ajá gbé lá ẹ̀jẹ̀ Nábótì, ni àwọn ajá yóò lá ẹ̀jẹ̀ rẹ, àní tìrẹ!’ ”

20. Áhábù sì wí fún Èlíjà pé, “Ìwọ ti rí mi, ìwọ ọ̀ta mi!”Ó sì dáhùn wí pé, “Èmi ti rí ọ, nítorí tí ìwọ ti tan ara rẹ láti ṣe búburú níwájú Olúwa.

21. ‘Èmi yóò mú ibi wá sórí rẹ. Èmi yóò sì mú ìran rẹ kúrò, èmi yóò sì ké kúrò lọ́dọ̀ Áhábù gbogbo ọmọdé ọkùnrin, àti ọmọ ọ̀dọ̀, àti òmìnira ní Ísírẹ́lì.

22. Èmi yóò ṣe ilé rẹ bí ilé Jéróbóámù, ọmọ Nébátì, àti bí ilé Bááṣà, ọmọ Áhíjà, nítorí ìwọ ti mú mi bínú, ìwọ sì ti mú Ísírẹ́lì ṣẹ̀.’

23. “Àti níti Jésébélì pẹ̀lú Olúwa wí pé: ‘Àwọn ajá yóò jẹ Jésébélì nínú yàrá Jésírẹ́lì.’

24. “Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Áhábù tí ó kú ní ìlú, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run yóò jẹ àwọn ẹni tí ó kú ní ìgbẹ́.”

1 Ọba 21