1 Ọba 2:14-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

14. Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.”Bátíṣébà sì wí pé, “Má a wí.”

15. Ó wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí o ti mọ̀, ti tèmi ni ìjọba náà. Gbogbo Ísírẹ́lì ti wò mí bí ọba wọn. Ṣùgbọ́n nǹkan yípadà, ìjọba náà sì ti lọ sí ọ̀dọ̀ arákùnrin mi, nítorí ó ti wá sọ́dọ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Olúwa wá.

16. Nísinsìnyí mo ní ìbéèrè kan láti bi ọ́, má ṣe kọ̀ fún mí.”Ó wí pé, “O lè wí.”

17. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ̀ṣíwájú pé, “Mo bẹ̀ ọ́, jọ̀wọ́ sọ fún Sólómónì ọba (Òun kì yóò kọ̀ fún ọ́) kí ó fún mi ní Ábíságì ará Súnémù ní aya.”

1 Ọba 2