11. Ó ti jọba lórí Ísírẹ́lì ní ogójì ọdún (40): ọdún méje (7) ni Hébúrónì àti ọdún mẹ́talélọ́gbọ̀n (33) ní Jérúsálẹ́mù.
12. Bẹ́ẹ̀ ni Sólómónì jókòó lórí ìtẹ́ Dáfídì baba rẹ̀, ìjọba rẹ̀ sì fi ìdí múlẹ̀ gidigidi.
13. Wàyìí, Àdóníjà ọmọ Hágítì tọ Bátíṣébà, ìyá Sólómónì wá. Bátíṣébà sì bi í pé, “Àlàáfíà ni o bá wa bí?”Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àlàáfíà ni.”
14. Nígbà náà ni ó sì fi kún un pé, “Mo ní ohun kan láti sọ fún ọ.”Bátíṣébà sì wí pé, “Má a wí.”