1 Ọba 10:22-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Ọba sì ní ọkọ̀ Tásísì kan pẹ̀lú ọkọ̀ Hírámù ní òkun. Ẹ̀ẹ̀kan ní ọdún mẹ́ta ni ọkọ̀ Tásísì ń dé, tí ó ń mú wúrà àti fàdákà, eyín-erin àti ìnàkí àti ẹyẹ-ológe wá.

23. Sólómónì ọba sì pọ̀ ní ọrọ̀ àti ní ọgbọ́n ju gbogbo àwọn ọba ayé lọ.

24. Gbogbo ayé sì ń wá ojú Sólómónì láti gbọ́ ọgbọ́n tí Ọlọ́run ti fi sí i ní ọkàn.

25. Bí ọdún ṣe ń gorí ọdún olúkúlùkù àwọn tí ń wá sì ń mú ẹ̀bùn tirẹ̀ wá, ohun èlò fàdákà àti ohun èlò wúrà àti ẹ̀wù, àti tùràrí olóòórùn dídùn, ẹṣin àti ìbááka.

26. Sólómónì sì kó kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin jọ; ó sì ní egbèje (1400) kẹ̀kẹ́ àti ẹgbàata (13,000) ẹlẹ́ṣin, tí ó fi pamọ́ sí ìlú kẹ̀kẹ́ àti pẹ̀lú rẹ̀ ní Jérúsálẹ́mù.

27. Ọba sì jẹ́ kí fàdákà pọ̀ ní Jérúsálẹ́mù bí òkúta, àti igi kédárì ni ó ṣe kí ó dàbí igi síkámórè tí ń bẹ ní àfonífojì fún ọ̀pọ̀lọpọ̀.

1 Ọba 10