1 Ọba 1:38-41 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

38. Nígbà náà ni Sadókù àlùfáà, Nátanì wòlíì, Bénáyà ọmọ Jéhóiádà, àwọn ará Kérétì àti Pélétì sì sọ̀kalẹ̀ wá wọ́n sì gbé Sólómónì gun ìbaka Dáfídì ọba wá sí Gíhónì.

39. Sádókù àlùfáà sì mú ìwo òróró láti inú àgọ́, ó sì dà á sí Sólómónì lórí. Nígbà náà ni wọ́n sì fọn fèrè, gbogbo àwọn ènìyàn sì ké pé, “Kí Sólómónì ọba kí ó pẹ́!”

40. Gbogbo ènìyàn sì gòkè tọ̀ ọ́ lẹ́yìn wọ́n ń fọn ìpè, wọ́n sì ń yọ ayọ̀ ńlá, tó bẹ́ẹ̀ tí ilẹ̀ mì fún ìró wọn.

41. Àdóníjà àti gbogbo awọn àlejò tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ gbọ́ ọ́ bí wọ́n ti ń jẹun tán, wọ́n ń gbọ́ ipè, Jóábù sì wí pé, “Kí ní ìtumọ̀ gbogbo ariwo nínú ìlú yìí?”

1 Ọba 1