1 Kọ́ríńtì 3:4-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ǹjẹ́ ẹ̀yin kì í ṣe ènìyàn lásán bí? Níwọ̀n ìgbà tí ẹ ba ń sọ pé, “Èmi ń tẹ̀lé Pọ́ọ̀lù,” àti ti ẹlòmíràn tún wí pé, “Èmi ń tẹ̀lé Àpólò.”

5. Jú gbogbo rẹ̀ lọ, kí ni Àpólò ha jẹ́, kí ni Pọ́ọ̀lù sì jẹ́, àwọn ìránṣẹ́ lásán, nípaṣẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin gbàgbọ́, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti fi fún olukúlúkù.

6. Èmi gbìn, Àpólò ń bomirin; ṣùgbọ́n Ọlọ́run ni ń mú ìbísí wá.

7. Ǹjẹ́ kì í ṣe ẹni tí ó ń gbìn nǹkan kan, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe ẹni tí ń bomirin; bí kò ṣe Ọlọ́run tí ó ń mú ìbísí wá.

8. Ẹni tí ó ń gbìn àti ẹni tí ó ń bomi rín ní ìrònú kan àti èrèdí kan, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹnìkọ̀ọ̀kan wa yóò gba èrè tirẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe é kárakára tó.

1 Kọ́ríńtì 3