1 Kọ́ríńtì 10:4-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Wọ́n mu nínú omi tí Kírísítì fi fún wọn. Wọ́n mu omi ẹ̀mí láti inú àpáta tí ó ń tẹ̀lé wọn, àpáta náà ni Kírísítì. Ó wà pẹ̀lú wọn nínú ihà náà, òun ni àpáta tí ń fi omi ẹ̀mí tu ọkàn lára.

5. Ṣíbẹ̀ṣíbẹ̀ lẹ́yin èyí, ọ̀pọ̀ nínú wọn ni kò ṣe ìgbọ́ràn sí Ọlọ́run. Òun sì pa wọ́n run nínú ihà.

6. Ẹ̀kọ́ tí a lè kọ́ yìí jásí àpẹrẹ fún wa, kí a má ṣe ní ìfẹ̀ sí àwọn ohun búburú gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn nínú ihà.

7. Kí ẹyin má ṣe sin ère òrìṣà gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe; gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ pé, “Àwọn ènìyàn náà jókòó láti jẹ àti láti mu, wọ́n sì dìde dúró láti jó.”

8. Bẹ́ẹ̀ ni kí àwa kí ó má ṣe ṣe àgbérè gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọn ti ṣe, tí ẹgbàá-mọ̀kànlá-lé-ẹgbẹ̀rún ènìyàn sì kú ní ọjọ́ kan.

9. Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin má ṣe dán Olúwa wò, gẹ́gẹ́ bí àwọn mìíràn nínú wọn ti dán an wò, tí a sì fi ejò run wọ́n.

1 Kọ́ríńtì 10