7. Àti àwọn arákùnrin Rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn:Jélíélì àti Ṣékáríà ni olórí.
8. Àti Bélà ọmọ Ásásì ọmọ Ṣémà, ọmọ Jóẹ́lì tí ń gbé Áróérì àní títí dé Nébò àti Baaliméónì.
9. Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àti wọ ihà láti odo Yúfúrátè; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ si i ní ilẹ̀ Gílíádì.