1 Kíróníkà 5:15-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Áhì, ọmọ Ábídélì, ọmọ Gúnì, olórí ilé àwọn baba wọn.

16. Wọ́n sì ń gbé Gílíádì ní Básánì àti nínú àwọn ìlú Rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbéríko Sárónì, ní agbégbé wọn.

17. Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn-ìdílé, ní ọjọ́ Jótamù ọba Júdà, àti ní ọjọ́ Jéróbóámù ọba Ísírẹ́lì.

18. Àwọn ọmọ Rúbẹ́nì, àti àwọn ọmọ Gádì, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé aṣà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ènìyàn o le ẹgbẹ̀rinlélógún dín ogójì, tí ó jáde lọ sí ogún náà.

19. Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hágárì jagun, pẹ̀lú Jétúrì, àti Néfísì àti Nádábù.

20. Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hágárì lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí ti wọn képe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.

21. Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ràkunmí ẹgbàámẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùnún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbàá, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn ún.

22. Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbékùn.

23. Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Mánásè ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Básánì títí dé Báálì-hérímónì, àti Ṣénírì àti títí dé òkè Hérímónì.

1 Kíróníkà 5