1 Kíróníkà 21:19-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Bẹ́ẹ̀ni Dáfídì sì gòkè lọ pẹ̀lú ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ tí Gádì ti sọ ní orúkọ Olúwa.

20. Nígbà tí Órínánì sì ń pakà lọ́wọ́, ó sì yípadà ó sì rí áńgẹ́lì; àwọn ọmọ Rẹ̀ mẹ́rẹ̀ẹ̀rin tí ó wà pẹ̀lú Rẹ̀ pa ará wọn mọ́.

21. Nígbà náà Dáfídì sì súnmọ́, Nígbà tí Órínánì sì wò tí ó sì rí, ó sì kúrò ní ilẹ̀ ìpakà ó sì doju bolẹ̀ níwájú Dáfídì pẹ̀lú ojú Rẹ̀ ní ilẹ̀.

22. Dáfídì sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó ni ibi ìpakà rẹ kí èmi kí ó sì lè kọ́ pẹpẹ fún Olúwa, kí àjàkálẹ̀-àrùn lórí àwọn ènìyàn lè dúró. Tàá fún mi ní iye owó kíkún.”

23. Órínánì ni ó sọ fún Dáfídì pé, “Gbà á! Jẹ́ kí Olúwa ọba mi kí ó ṣe ohun tí ó dára lójú Rẹ̀. Woó, èmí yóò fún ọ ní àwọn màlúù fún ẹbọ ọrẹ ṣiṣun, àti ohun èlò ìpakà fún igi, àti ọkà fún ọrẹ oúnjẹ. Èmi yóò fun ọ ní gbogbo èyí.”

1 Kíróníkà 21