1 Kíróníkà 2:20-29 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Húrì ni baba Úrù, Úrù sì jẹ́ baba Bésálélì.

21. Nígbà tí ó yá, Hésírónì sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Mákírì baba Gílíádì (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Ṣégúbù.

22. Ṣégúbù sì jẹ́ bàbá Jáírì, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́talélógún ní ilẹ̀ Gílíádì.

23. (Ṣùgbọ́n Gésúrì àti Árámù sì fi agbára gba Hafoti Jáírì, àti Kénátì pẹ̀lú gbogbo agbégbé Rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Mákírì Baba Gílíádì.

24. Lẹ́yìn tí Hésírónì sì kú ni Kélẹ́bù Éfúrátà, Ábíà ìyàwó Rẹ̀ ti Hésírónì sì bí Áṣúrì baba Tẹ́kóà fún un

25. Ọmọ Jéráhímélì àkọ́bí Hésírónì:Rámà ọmọ àkọ́bí Rẹ̀ Búnà, Órénì, óṣémù àti Áhíjà.

26. Jéráhímélì ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ Rẹ̀ ń jẹ́ Átarà; ó sì jẹ́ ìyá fún Ónámù.

27. Àwọn ọmọ Rámà àkọ́bí Jéráhímélì:Másì, Jámínì àti Ékérì.

28. Àwọn ọmọ Ónámù:Ṣámáì àti Jádà.Àwọn ọmọ Ṣámáì:Nádábù àti Ábísúrì.

29. Orúkọ ìyàwó Ábísúrì ni Ábíháílì ẹni tí ó bí Áhíbánì àti Mólídì.

1 Kíróníkà 2