1 Kíróníkà 2:1-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì.Réúbẹ́nì, Símónì, Léfì, Júdà, Ísákárì, Ṣébúlúnì,

2. Dánì, Jóṣẹ́fù, Bẹ́ńjámínì; Náfítanì, Gádì: àti Áṣérì.

3. Àwọn ọmọ Júdà:Érì, Ónánì àti Ṣélà, àwọn mẹ́tẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kénánì, ọmọbìnrin Súà Érì àkọ́bí Júdà, ó sì burú ní ojú Olúwa; Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.

4. Támárì, aya ọmọbìnrin Júdà, ó sì bí Fárésì àti Ṣérà sì ní ọmọ márùn ún ní àpapọ̀

5. Àwọn ọmọ Fárésì:Hésírónì àti Hámúlù.

6. Àwọn ọmọ Ṣérà:Ṣímírì, Étanì, Hémánì, Kálíkólì àti Darà, gbogbo wọn jẹ́ márùn ún.

7. Àwọn ọmọ Kárímì:Ákárì, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Ísírẹ́lì nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.

8. Àwọn ọmọ Étanì:Áṣáríyà

9. Àwọn ọmọ tí a bí fún Hésírónì ni:Jéráhímélì, Rámù àti Kélẹ́bù.

1 Kíróníkà 2