10. Jóábù ri wí pé àwọn ìlà ogun wà níwájú àti ẹ̀yìn òun; Bẹ́ẹ̀ ni ọmọ ogun tí ó dára ní Ísírẹ́lì, o sì tẹ́ ogun wọn sí àwọn ará Ṣíríà.
11. Ó fi ìyókù àwọn ọkùnrin náà sí abẹ́ àkóso Ábíṣáì arákùrin Rẹ̀, a sì tẹ́ wọn kí wọn dojúkọ àwọn ará Ámónì.
12. Jóábù wí pé Tí àwọn ará Ṣíríà bá le jù fún mi, nígbà náà, ìwọ ni kí o gbà mí; Ṣùgbọ́n tí àwọn ará Ámónì bá le jù fún ọ, Nígbà náà èmi yóò gbà ọ́.
13. Jẹ́ alágbára kí ẹ sì jẹ́ kí a jà pẹ̀lú ìgboyà fún àwọn ènìyàn wa àti àwọn ìlú ńlá ti Ọlọ́run wa. Olúwa yóò ṣe ohun tí ó dára ní ojú Rẹ̀.