1 Kíróníkà 15:24-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Ṣébéáníá, Jóṣáfátì, Nétanélì, Ámásáyì, Ṣekaríyà, Beniáyà àti Élíásérì ní àwọn àlùfáà, ti o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Édómù àti Jéhíyà ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùsọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.

25. Bẹ́ẹ̀ ni Dáfídì àti àwọn àgbààgbà Ísírẹ́lì àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Édómù, pẹ̀lú inú dídùn.

26. Nítori Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Léfì énì tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi sé ìrúbọ.

27. Nísinsìn yìí Dáfídì sì wọ aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, gẹ́gẹ́ bí akọrin, àti Kenaníyà, ẹnití ó wà ní ìkáwó orin kíkọ àwọn akọrin. Dáfídì sì wọ aṣọ ìgúnwà fun fun.

1 Kíróníkà 15